Loading...
Larger font
Smaller font
Copy
Print
Contents

ISE ISIN ONIGBAGBO

 - Contents
  • Results
  • Related
  • Featured
No results found for: "".
  • Weighted Relevancy
  • Content Sequence
  • Relevancy
  • Earliest First
  • Latest First
    Larger font
    Smaller font
    Copy
    Print
    Contents

    Àwọn Àwáwí tí Kò Lẹ́sẹ̀ Nílẹ̀

    Nígbà tí Jésù padà lọ, ó fi olúkúlùkù sílẹ̀ pẹ̀lú iṣẹ́ ẹ rẹ̀, “kò sí ohun kan láti ṣe” jẹ́ àwáwí tí kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀. “Kò sí ohun kan láti ṣe” jẹ́ ìdí tí ìdánwò láarin ará lọ́kùnrin àti lóbìnrin, nítorí èṣù yóò wá kún inú àwọn onímẹ́lẹ́ pẹ̀lú èrò o rẹ̀, yóò sì mú wọn ṣiṣẹ́….”Kò sí ohun kan láti ṣe” ń ní ìjẹ́rì í búburú wá tako àwọn ará, àti ìyapa sínú ìjọ ti Kristi. Jesu wí pé, “ẹni tí kò kójọ pẹ̀lú ù MI n fọ́nká lóde.”- Review and Herald, March 13, 1888.IIO 108.1

    Ará lọ́kùnrin àti lóbìnrin, ọ̀pọ̀ nínú u yin ń ṣe àwáwí láti yọ ara a wọn sílẹ̀ nínú íṣẹ́ lórí ẹ̀bẹ̀ níti àìlágbára láti ṣiṣẹ́ fún ẹlòmíràn. Ṣùgbọ́n ṣé Ọlọrun ṣe ọ́ ní aláìlágbára tó bẹ́ẹ̀? Ṣé kì i ṣe àìṣe ohun kan ló ṣokùnfà àìlera à rẹ, èyí tí ó wáyé nípa ohun tí o mọ̀-ọ́n —mọ̀ yàn? Ṣé ko fún ọ ní ẹ̀bùn kan ó kéré tán láti túnṣe, kì í ṣe fún ìrọ̀rùn àti ìgbádùn-un rẹ̀, ṣùgbọ́n fún Òun? Ṣé o rí jíjẹ́ ìránṣẹ́ Ọlọ́run bí ọ̀ràn-an-yàn láti mú èrè wá fún-Un? Ṣé o kò tí ì ṣe àìkàsí àwọn ànfààní láti tún àwọn agbára à rẹ ṣe sí èyí? Ó jẹ́ òótọ́ pé díẹ̀ ni ó ti ní ìmọ̀lára ti iṣẹ́ ẹ wọn sí Ọlọrun.-Testimonies, vol.5, p.457.IIO 108.2

    Ọ̀pọ̀ ló ní èrò o pé tí ìgbé ayé e wọn bá jẹ́ ṣí ṣiṣẹ́, nínú ìgbé ayé òwò o wọn, wọn kò lè ṣe ohunkóhun fún ìgbàlà àwọn ọkàn, kò sí ohun kan láti fi tẹ iṣẹ́ Olùgbàlà a wọn síwájú. Wọ́n sọ pé wọn kò lè ṣe àwọn ohun kan nípa pínpín sí méjì, àti nípa bẹ́ẹ̀, wọ́n yípadà kúro nínú àwọn iṣẹ́ ìsìn àti láti lo iṣẹ́ ìsìn-in wọn, wọ́n sì bo ara wọn mọ́lẹ̀ nínú ayé , wọ́n mú iṣẹ́ òòjọ́ ọ wọn ní ọ̀kúnkúndùn, wọ́n sì gbàgbé Ọlọ́run, Kò sì ní inú dídùn sí wọn. Tí ẹnikẹ́ni bá wà nínú iṣẹ́ níbi tí wọn kò lè tẹ̀síwájú nínú ìgbé ayé ọ̀run àti ìjẹ́ mímọ́ pípé ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run, wọ́n gbọdọ̀ yípadà sí iṣẹ́ èyí tí wọn yóò lè ní Jésù pẹ̀lú u wọn ní wákàtí gbogbo.-Testimonies, vol.2, pp.233,234.IIO 108.3

    Larger font
    Smaller font
    Copy
    Print
    Contents